Categories
Latori tabili Paitor

Njẹ iwo gba ore-ofẹ rẹ lasan bi?

Olufẹ: ki ore-ofẹ, aanu ati alaafia jẹ tirẹ titilailai lati ọdọ Ọlọrun Baba wa ati Jesu Kirisiti Oluwa wa. Inu mi dun lati ki ọ kaabọ sinu osẹ miran ninu osu Ogun 2020. Mo si gbadura pe ki Ọlọrun se iṣe ti yo mu inu rẹ dun ninu aye rẹ ni osẹ na ati pe ki o ma se fi ore-ofẹ rẹ sofo, ni orukọ Jesu. Amin.

Nibayi mo gba adura yi fun ọ nitoripe ifẹ ọkan mi ni pe ki aye rẹ jẹ ifarahan ore-ofẹ ati didara Ọlọrun. Nje iwo tile ti ri ore-ọfẹ re gba bi? Ti o ba jẹ ọmọ Ọlọrun, a jẹ wipe o ti gba ore-ọfẹ re niyẹn. Idi si ni wipe bibeli sọ wipe nipa ore-ọfẹ rẹ ni a gbawala. Eyi tunmo si pe nitori iṣẹ ti Ọlọrun se ati nitori nkan ti O fi fun wa ni a se gbawala lọwọ ẹṣẹ wa, lọwọ esu ati lọwọ iparun ayeraye. (Wo: Efesu 2:1-10)

Amọ o, o wa yẹ ki nkan ti Ọlọrun se fun wa ati eyi ti O fun wa jẹyọ ninu aye wa. Nkan ti mo n sọ ni pe o yẹ ki o farahan pe lotitọ ni Ọlọrun ti gbawala, tunwabi, ti O si tun gba akoso aye wa. Fun apẹẹrẹ, ninu lẹta rẹ si awọn ara Tẹsalonika, Pọọlu sọ wipe, “Nitori ẹyin tikarayin mọ, ara, pe ibẹwo wa si yin kii se lasan.” (1Tẹsalonika 1:4-10) Ki ni idi ti o fi sọ eyi si awọn ara wọnyi? Idi ni pe o ri ifarahan ore-ọfẹ Ọlọrun ninu aye wọn. Gẹgẹ bi o ti fi han wa ni ori akọkọ lẹta yi, ọrọ ore-ọfẹ Ọlọrun ti wọn gba ko wọ inu aye wọn lailai yi pada. O yi wọn pada. O jẹ ki wọn yipada kuro ninu ibọriṣa lati sin Ọlọrun ati lati duro de ipadabọ Ọmọ rẹ, Jesu Kirisiti. Yatọ si eyi, o yi wọn pada si awokọse rere ọpọlọpọ awọn ọmọ Ọlọrun nibomiran. Nitorina, ore-ọfẹ Ọlọrun ti wọn rigba ko ja si asan ninu aye wọn. (Wo: 1Tẹsalonika 1:4-10)

Lafikun, Pọọlu, ninu lẹta rẹ si awọn ara Korinnti, sọ eyi nipa ara rẹ: “…ore ọfẹ rẹ ti a fi fun mi ko si jẹ asan…”
(1Korinnti 15:10) Eyi tunmọ si pe ore-ọfẹ Ọlọrun mu ifẹ rẹ wa si imuṣẹ ninu aye rẹ. O ṣọ di irufẹ eniyan ti Oun fẹ ki o jẹ ati pe o tun fun ni okun lati se awọn nkan ti O fẹ ki o se. Njẹ a wa le sọ eyi nipa awa na bi? Njẹ a le sọ wipe ore-ọfẹ Ọlọrun ti awa na rigba ti n sọ wa di iru eniyan ti Oun fẹ ki a jẹ bi?

Ti ore-ọfẹ Ọlọrun ti a ti rọ ojo rẹ sinu aye wa ko ba ma sọ wa di iru eniyan ti O fẹ ki a jẹ, o tunmọ si pe a n fi sofo niyẹn. Bawo si ni eyi se se e se? Yo se e se ni iwọn igba ti a ba ti kọ lati se amulo ore-ọfẹ rẹ ni ọna ti o yẹ, ti o si tun peye. Ore-ọfẹ Ọlọrun fun igbala, igbe aye ododo ati iṣẹ isin ti ẹmi ni a ti fi fun wa lọfẹ. A ti fi fun wa ninu ọrọ rẹ, ninu Ẹmi rẹ ati ninu ibasepọ awọn ọmọ rẹ. Eyi tunmọ si pe a le gbadun ore-ọfẹ Ọlọrun nipa fifi aye gba iṣẹ iranṣẹ ọrọ rẹ ati ti Ẹmi rẹ ati ti awọn eyinyan rẹ ti O ti gbin sinu aye wa.

Sugbọn, bi o tilẹ jẹ wipe a ti fun wa ni awọn nkan wọnyi lọfẹ, wọn ko ni kan dede ṣiṣẹ fun iyipada ọtun ninu aye wa ti a ko ba se amulo wọn ni ọna ti o yẹ. Nkan ti mo n sọ ni pe ti a ko ba mu iṣẹ iranṣẹ ọrọ Ọlọrun lọkunkundun, ki a dirọ mọ ṣinṣin lati se nkan ti o n sọ fun wa, ki a si ma rin ninu imọlẹ rẹ, aye wa ko ni fi ore-ọfẹ Ọlọrun han. Lafikun, ti a ko ba fi aye gba Ẹmi Ọlọrun lati gbakoso aye wa ati awọn nkan ti a n se, ki a gbọkanle fun ohun gbogbo ti a nilo, aye wa ko ni ri bi Ọlọrun se fẹ ki wọn ri ninu aye yi. Nibakanna, ti a ko ba se amulo ti o yẹ ati ti o si peye ibasepọ awọn ọmọ Ọlọrun ti o wa ni aye wa, a ko ni dagba soke bi o se yẹ ki a dagba soke lati gbe aye yi bi o se yẹ ki a gbe.

Nje gẹgẹbi mo se sọ tẹlẹ, niwọn igba ti a ko ba ti ma fi gbogbo igba dabi Ọlọrun se fẹ ki a ri, ki a si tun ma se gbogbo nkan ti O fẹ ki a ma se, a n fi ore-ọfẹ rẹ ati laala Ẹmi rẹ lori aye wa sofo niyẹn. Ṣe a wa le fi ore-ọfẹ re sofo bi eyi ki a si tun ri oriyin gba lọdọ rẹ bi? Njẹ eyi gan ko ni fẹ fihan pe a ko fi igba kankan gba ore-ọfẹ sinu aye wa ati pe a kan n dibọn ni? Laisaroye lọpọ, mo fẹ ki o mọ pe ti o ba ti ri ore-ọfẹ re gba, o yẹ ki o suyọ ninu aye rẹ. Ti ko ba si ma suyọ, o yẹ ki o bẹrẹ si ni bere awọn ibeere kan ti o se pataki lọwọ ara rẹ lori iha ti o kọ si amulo ore-ọfẹ yi. Adura mi ni pe ki Ẹmi Ọlọrun si oju re lati ri awọn ibi ti o ti n kuna, ki O si tun ran ọ lọwọ lati bẹrẹ si ni se ohun ti o tọ pẹlu ore-ọfẹ rẹ.

Ọsẹ ire o.

Copyright © 2020, Reality Desk, a ministry of Alaythia Bible Church –This material is the sole property of Reality Desk. It may be copied for personal non-commercial use only in its entirety free of charge. All copies must contain this copyright notice. Please direct any questions you may have to alaythiabiblechurch@gmail.com/alaythia4all@gmail.com or call: 08037592851 (WhatsApp Number: 07085711280)
Lati owo: J.O. Lawal | Ojo: Ogun 09, 2020 | Atelera: Latori tabili Paito | Nomba: Vol. 9, No. 13

Categories
Fire in my Bones

Don’t quit

“If your boss is angry at you, don’t quit! A quiet spirit can overcome even great mistakes.”

(Eccl 10:4NLT)

I once worked with a boss that seemed at the time to take delight in ridiculing the jobs of his subordinates. He would just find a way to diminish the relevance of whatever you have done, leaving you with a feeling that you were useless, irresponsible and incapable of using your head to solve simple problems. So, many who came to work with us then in the office, simply because they were attracted by the outward glamour of all we were doing, could not cope for more than two months before they left. And that was because our boss was a very hard to please man. You know, he was the kind that would not mind if you put your life on the line in order to accomplish the measure of excellence he desired.

Categories
Pastor's Desk

The sure way to prosperity

Beloved: Blessed be the God and Father of our Lord Jesus Christ who, in His immense kindness, has safely brought us into the eighth month of this year, the month of August. And my prayer is that our lives will know nothing but progress everyday of the month, in Jesus’ name. Amen.

Now one sure way to experience progress in every area of our lives is to take the word of God seriously. This is one thing that God emphasized to Joshua, as He commissioned him to lead the children of Israel into their inheritance. He said to him:

Categories
Latori tabili Paitor

Ona isorire ti o daju

Olufe: Olubukunfun ni Olorun ati Baba Jesu Kirisiti Oluwa wa, Eni ti O mu wa wo inu osu kejo odun yi, osu Ogun, lalaafia ninu ojurere re ti o ga. Adura mi si ni pe aye wa ko ni mo ohunkohun to yato si ilosiwaju ninu osu na, ni oruko Jesu. Amin.

Nje ona kan to daju lati ni iriri ilosiwaju ni gbogbo ona aye wa ni ki a mu oro Olorun ni okunkundun. Nkan eyokan yi ni Olorun te mo Josua leti nigba ti O n pase fun lati dari awon omo Israeli lo sinu ile ini ti O fi fun won. O so fun pe:

Categories
Fire in my Bones

Put a knife to your throat

“When you sit to dine with a ruler, note well what is before you, and put a knife to your throat if you are given to gluttony. Do not crave his delicacies, for that food is deceptive.”

(Prov 23:1-3NIV)

There is nobody in this life that will not at one time or the other need the help of others to go from where he is to where he is supposed to be. But it is important in seeking help that we look to God alone and not to men. That is because, first, if God does not help us, there is no one that can help us (2Kings 6:26-27). If God does not move people’s heart to help us or lift us, even if we live in a corner of their nostrils and they have all that it takes to help us, they will still not remember us or think of doing anything to help us.

Categories
Pastor's Desk

The nature of God’s judgment

Beloved: grace and peace to you from God our Father and Jesus Christ our Lord. Welcome to the last week of the month of July 2020. My prayer is that none of the good things that are meant for you in the month will elude you, in Jesus’ name. Amen.

Now, as one considers the terrible situation of things in this country, especially in the light of the recent allegations of fraud and corruption against some of our leaders, there is every tendency that he will be moved to ask God to swiftly judge all those who are involved and several others who are making it difficult for the nation to progress. And it is clear from scriptures that God will certainly judge people for all such acts of wickedness, not just at the end of this age but also right here on earth (1Sam 3:13; 1Kings 14:7-11). But those of us who are believers and who are also probably wishing that God will be quick to set things right in the country must also not forget that God does not judge things the way people do.

Categories
Latori tabili Paitor

Irisi idajo Olorun

Olufe: ki ore ofe ati alaafia je tire lati odo Olorun Baba wa ati Jesu Kirisiti Oluwa wa. Mo ki o kabo sinu ose ti o pari osu Agemo 2020. Adura mi si ni pe ikankan ninu ohun rere ti o ye ki o je tire losu na ko ni fo o ru, loruko Jesu. Amin.

Nje ti eniyan ba wo bi nkan se polukumusu ni orile-ede yi lakoko yi, paapajulo ti eniyan ba wo gbogbo awon esun iwa ibaje ati ti sise owo ilu ni basubasu ti a fi n kan die lara awon olori wa laipe yi, o se e se ki a fe ki Olorun gbera ni kiakia lati se idajo gbogbo awon ti oro na kan ati awon miran bi tiwon ti won n je ki o soro ki orile-ede wa ni itesiwaju. A si ri daju ninu iwe mimo pe Olorun ma n se idajo awon eniyan fun irufe awon iwa ika wonyi, eyi ti ki i se ni opin aye yi nikan sugbon ninu aye yi gan (1Samueli 3:13; 1Awon Oba 14:7-11). Sugbon awon ti a je onigbagbo, ti o si tun se e se pe awa na n fe ki Olorun mu nkan bo si otun ni kiakia ni orile-ede yi, ko gbodo gbagbe pe Olorun ko ki i se idajo bi awa eniyan ti ma n se.

Categories
Fire in my Bones

Why do you choose them?

“After the wall had been rebuilt and I had set the doors in place, the gatekeepers and the singers and the Levites were appointed. I put in charge of Jerusalem my brother Hanani, along with Hananiah the commander of the citadel, because he was a man of integrity and feared God more than most men do.”

(Neh 7:1-3NIV)

When Nehemiah was governor of the land of Judah, he once needed to appoint someone over the city of Jerusalem. And interestingly, it was his brother, Hanani, that he appointed. But why did he appoint Hanani over Jerusalem? Was it because he was his brother? No! As the text above shows us, the reason Nehemiah appointed Hanani over Jerusalem was that he was a man of integrity and feared God more than most men do.

Categories
Others Pastor's Desk

A point of reference for good

Beloved: grace and peace to you from God our Father and Jesus Christ our Lord. It is with great delight that I welcome you into another week of the month of July 2020. And I pray that God will perfect all that concerns you and make your life a point of reference for good things, in Jesus’ name. Amen.

As we see in the bible, the very first king God ordained over the Israelites was Saul. But after the record of his death, nothing serious is mentioned about him again. Why? It was because he did not live an exemplary life. Yes, he reigned for forty years. But those forty years meant nothing to God, for they were not lived to honour Him.

Categories
Latori tabili Paitor Yoruba (Fire in my Bones)

Aritokasi ni rere

Olufe: ki ore-ofe ati alaafia je tire lati odo Olorun Baba wa ati Jesu Kirisiti Oluwa wa. Pelu idunnu ni mo se ki o kabo sinu ose miran ninu osu Agemo 2020. Mo si gbadura pe ki Olorun se ni asepe gbogbo ohun ti n se tire, ki o si tun se aye re ni aritokasi ni rere, ni oruko Jesu. Amin.

Gege bi a se ri ninu bible, oba akoko paa ti Olorun yan sori awon omo Isiraeli ni Soolu. Sugbon leyin akosile iku re, a ko so nkan miran to se pataki nipa re mo. Ki si ni idi? Idi ni wipe ko gbe igbe aye arikose si rere. Lotito, ogoji odun ni o fi joba. Sugbon gbogbo ogoji odun yi ko jamo nkankan loju Olorun nitoripe ko lowon lati bowo fun Olorun.